Skip to main content

Kọ́lẹ́ẹ́jì Onígbá Méjì Láti Ọwọ́ Fẹ́mi Ọ̀ṣọ́fisan: Ìfáárà

Bí a Tilẹ̀ Ń Sunkún, A Kìí Ṣài Ríran! 


Lọ́dun 1975 ni wọ́n kọ́kọ́ tẹ Kolera Kolej, àkọlé tí a túmọ̀ sí Kọ́lẹ́ẹ̀jì Onígbá Méjì nínú ìwé yìí. Ilé iṣẹ́ aṣèwé New Horn Press ní ìlú Ìbàdàn ló gbé e jádé. Òun sì ni ìwé ìtàn aláròsọ àkọ́kọ́ láti ọwọ́ Fẹ́mi Ọ̀ṣọ́fisan, ẹni tí gbogbo olóye ènìyàn mọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀jọ̀gbọ́n àti òǹkọ̀wé jàǹkàn. Eré aláṣehàn lórí ìtàgé ni Ọ̀jọ̀gbọ́n Ọ̀ṣọ́fisan gbajúmọ̀ fún. Ṣàṣà ènìyàn ló mọ Ọ̀ṣọ́fisan ní olùkọ̀tàn. Kòtóǹkan ni iye ẹni tó mọ Ọ̀jọ̀gbọ́n Ọ̀ṣọ́fisan gẹ́gẹ́ bí eléwì. Ṣùgbọ́n òǹkàwé tó bá fojú inú wo Kólẹ́ẹ̀jì Onígbá Méjì yóò rí i pé àṣehàn pọ̀ fún àwọn ẹ̀dá inú ìtàn náà; kódà bárakú ni ìṣe onídan jẹ́ fún èyí tó pọ̀ jù nínú àwọn èrò Onígbáméjì àti Oríle Iyá. Síwájú sí i, kò sí bí òǹkàwé kò ṣe ní kíyèsí ipa pàtaki ti ọ̀jọ̀gbọ́n akéwì, ẹ̀dá tó fẹ́ràn ajá rẹ̀ ju ènìyàn lọ, kó nínú ìtàn yìí. Ní tòótọ̀, ẹni wa fẹ́ràn obínrin dé góńgó; ṣùgbọ́n ìfẹ́ tí ó ní sí ajá rẹ̀ tayọ, ó ju góńgó lọ. Ìtumọ àlàyé tí mò ń ṣe ni pé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé sísọ ni a sọ ìtàn inú Kólẹ́ẹ̀jì Onígbá Méjì, ọgbọ́n ìfihàn ìṣe àti ìrònú ìkéwì fìdí mulẹ̀ síbẹ̀. Dájúdájú, ìtàn tó lárinrin ni. Àràmàdà ẹ̀dá pọ̀  yanturu ní Onígbáméjì. Bí ṣàpà ti ń dàpọ̀ mọ́ lúrú, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará ìlú ń kó o jẹ wọ̀mù.  Onírúurú ìṣe, ọ̀pọ̀lọpọ̀ èyí tó já sí èṣe àti àṣìṣe, ló kún inú ìtàn yìí: ìdìbó àkọ́kọ́, ìdásílẹ̀ ìgbìmọ̀ aṣòfin, kíkọ àdéhùn ìpìlẹ̀, ìṣẹ̀dá orin ìwúrí orílẹ̀ èdè, ìfilọ́lẹ̀ àsiyá ẹyẹ, ìfìjọbalọ́lẹ̀. 

Ìtàn inú ìwé yìí fi yé wa pé orílẹ̀ èdè kan ń bẹ tí ó ń jẹ́ Orílé Iyá, níbi tí yunifásitì olókìkì kan gbé wà. Lójijì, àjàkálẹ̀ àrùn kan tí kò lẹ́rọ̀ bẹ́ sílẹ̀. Bí àmódi náà ti ń mú àwọn èrò fásitì ṣu láìdákẹ́, bẹ́ẹ̀ ló ń mú wọn bì títí ẹ̀mí yóò fi jábọ́. Láti dẹ́kun ìtànkálẹ̀ àrùn tí kò gbóògùn yìí, àwọn aláṣẹ Orílé Iyá sọ yunifásitì ọ̀hún—Kọ́lẹ́ẹ́jì Onígbáméjì—di olómìnira àpàpàndodo. Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ìdáǹdè tí ibùgbé ìmọ̀ giga yii kò bèèrè fún di àjẹmógún fún un. Ṣùgbọ́n ìtura kò dé. Kàkà kó sàn ní Kọ́lẹ́ẹ́jì Onígbáméjì lẹ́yìn ìtúsílẹ̀ nínú ìgbèkùn irọ́, ṣe ni àbìlù ń yí lu’ra wọn. Bí ìgbà tí ó jẹ́ pé àìsàn onígbáméjì gan an ló so ìjọba ró ni ọ̀ràn náà rí.

Àlọ́ àpamọ̀ kọ́ lèyì. Bẹ́ẹ̀ ni kìí ṣe àpagbè. Ohun tá à mọ̀, òun laà mọ̀. Irúfẹ́ ìtàn wo wá ni Kólẹ́ẹ̀jì Onígbá Méjì? Ó dá ni lóju pé ìtàn olówe ni. Òwe náà sì yà sọ́nà púpọ̀. Bó ti ń pòwe ìṣẹ̀lẹ̀,  ló ń pòwe ìṣèlú, ló tún ń pòwe àróbá. Àróbá lásán sì kọ́, àróbá ìṣẹ̀lẹ̀ tòun tìṣèlú ni. Ìtàn inú Kólẹ́ẹ̀jì Onígbá Méjì kìí ṣe aláwòmọ́, nítorí pé kò sí ìlú tàbí orílẹ̀ kan tí a lè pé ní àwòkọ ìtan inú ìwe yìí. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹ̀dá ìtàn náà ń hùwà bí ẹ̀yà Yorùbá—àwọn kan nínú wọn tilẹ̀ lóríkì—ìṣesí gbogbo wọn, ìbáṣepọ̀ wọn, ìhà tí wọ́n kọ sí àkokò àti ìgbà, kò jọ ti ẹ̀yà kan pàtó. Ìpèsè fún ọjọ ọ̀la ṣe àjèjì sí wọn. Kò sí òpin, kò sí ìbẹ̀rẹ̀; agbedeméjì ni gbogbo nǹkan. Wọn kìí ṣe orò tàbí ọdún kankan nínú ayé ìtàn tí ìwé yìí gbé kalẹ̀. Kàyèfí ni gbogbo nǹkan wọn. Ibi mánigbàgbé pọ̀ bí ìgbẹ́ nínú ìtàn yìí: àjàkálẹ̀ àrùn gbẹ̀mí àìníye, láti orí àwọn aláṣẹ ìjọba títí lọ bá àwọn mẹ̀kúnnù tí kò lágbára; ìfipáṣèlú dàbí àdámọ́; bí ìjọba kan ti ń wó lulẹ̀ lòmíràn ń gun orí àléfà láì bìkítà fún ìlànà òfin; ọ̀wọ́n oúnjẹ gbòde; ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ aláìṣẹ̀ ni ìjoba kò-sẹ́ni-tí-yó-bi-wà jù sínú túbu làì wẹ̀yìn. Kí a má a sọ orílẹ̀ èdè ẹni sóko ọfà fún àníyàn orílẹ̀ èdè míràn kò tu irun kan lára àwọn olórí Kọ́lẹ́ẹ̀jì Onígbáméjì. Òǹkàwé tó bá gbẹ́kẹ̀ lé eléwì tó fẹ́ máa fi àkọsílẹ̀ ewì ṣe ìjẹ́rìí ọkàn rí i ní kòpẹ́kòpẹ́ pé wérewère òun náà pọ.  Ni Kọ́lẹ́ẹ̀jì Onígbáméjì, àtìwọ̀fà, àtolówó, ète ìtànjẹ ni wọ́n ń pa láìdákẹ́. Ẹ̀tọ́, òótọ́, ati irọ́; kò yàtọ̀; ẹ̀ràn àti ẹ̀tàn di ọ̀kan; ọgbọgba sì ni irọ́ àti àwàdà. Bí àjàkálẹ̀ àrun ti ń gbé olóri fásitì ṣánlẹ̀ ni gbangba, eré onídan ni asọ̀tàn àti àwọn akóròyìnjọ pè é fún òǹkàwé. Rúdurùdu gbilẹ̀ lọ rẹpẹtẹ. 


Adélékè Adéẹ̀kọ́

Comments

Popular posts from this blog

One Thought About Textual Beginnings: Ìbà

ÌJÚBÀ or ÌBÀ (noun); JÚBÀ (verb)   The initial gestures rendered to acknowledge authority figures, sacral or secular, to which a performance production owes its textual and institutional provenance constitute the ìjúbà (ìbà). The conventional words and motions thus presented demarcate the commencement of an iteration, pay homage to sources of influence and inspiration, praise past patronages, solicit audience support and understanding, wish failure for opposing will and interests, and outline the production’s goals. HISTORY Two paths stand out in the historical understanding of ìjúbà: one follows the older, text based line in translation manuals and dictionaries, and the other issues from scholarly studies of performance traditions. Although they are more recent and offer longer overviews that extend far back into mythical times, scholarly studies of ìjúbà lean heavily on old traditions recounted in explanations of contemporary enactments, mainly of egúngún and gẹ̀lẹ̀de...

Aṣọ Tòun Tènìyàn

Aṣọ Tàbí Ènìyàn? Lẹ́dà kan, mo gbọ́ pé, aṣọ ńlá kọ́ lènìyàn ńlá. Lẹ́dà kejì wọ́n tún fi yé mi pé aṣọ là ńkí, a à kí ‘nìyàn. (Ẹnu kòfẹ́sọ̀ àgbà kan ni mo tí kọ́kọ́ gbọ́ eléyìí ní nńkan bí ogún ọdún sẹ́hìn.) Èwo ni ká wá ṣe o? Èwo ni ká tẹ̀lé? Èwo ni ká gbàgbọ́. Gbólóhùn méjèèjì ha le jẹ́ òótọ́ bí? Àtakò kọ́ rèé! Ó dá mi lójú pé àfiwé ni gbólóhùn méjèèjì. A tilẹ̀ lè pé wọ́n lówe. Gbogbo wa la sì mọ̀ pé àfiwé kìí ṣe òfin. Àfiwé yàtọ̀ sí ìṣẹ̀dálẹ̀. Òwe kìí ṣe orò. Àfiwé le jẹ́ àbàláyé. Ṣùgbọ́n ọgbọ́n tàbí ìmọ̀ tí àfiwé bá gbéró máa ńyí padà lóòrè kóòrè. Òjó yàtọ̀ sí òjò. Mẹ́táfọ̀ yàtọ̀ sí òtítọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òtítọ́ lè farasin sínú mẹ́táfọ̀. Ẹ̀ràn yàtọ̀ sí irọ́.   Kò sí ẹ̀dá alààyè àti olóye kankan tí kò mọ̀ pé aṣọ kìí ṣe ènìyàn, tàbí wí pé ènìyàn yàtọ̀ sí aṣọ. Dídá lènìyàn ńdá aṣọ tàbí ẹ̀wù. A kìi dá ènìyàn bí ẹni ńdáṣọ. Ènìyàn lè wọ aṣọ tàbí ẹ̀wù. Èmi kò rò pé aṣọ lè wọ ènìyàn bí è...

Ebenezer Táíwò Adéẹ̀kọ́: 20 Years After & Notes Towards a Memoir

Ebenezer Táíwò Adéẹ̀kọ́ | 1918-2000 My father, E. Táíwò as he was called by many, left his home town at about the age of eight with something like a second grade education in his pocket. I am talking of Òdoláamẹ́sọ̀ of late 1920s to early 1930s. First, he moved to Ìjẹ̀bú Òde (Metropolitan Ìjẹ̀bú) to live with his uncle (the late S.J.O. Òtúbúṣẹ̀n, alias Bàbá Télọ̀) who realized quickly that schooling was not this boy’s thing and sent him further away to Lagos (!) to learn carpentry, one of the newer (historically speaking) building trades. After finishing his apprenticeship successfully and working for a while in Lagos, he followed the call of other relatives to move further away to Kano, in the “land of the Hausa” as we used to refer to Northern Nigeria generally even in my own childhood of the 1960s in south western Nigeria.  At the end of WWII, during which he worked as a rifle carpenter in Kano, he returned south to Ìbàdàn, where he lived the rest of his life....