Skip to main content

Ikú. Ọ̀fọ̀. Arò


Ó Dígbà O, Ọ̀rẹ́ẹ̀ Mi 
Photo: Diípọ̀ Oyèlẹ́yẹ

Ikú lòpin àwa ènìyàn, àtì’wọ̀fà, àt’olówó, ikú lòpin àwa ènìyàn. 
-- Yusuf Ọlátúnjí

Igbèsè nikú, kò sẹ́ni tí ò níí san! 

Ikú lòpin ohun gbogbo.

Ènìyàn ò sunwọ̀n láàyè, ọjọ́ a bá kú làá dère.

Òkú ò mọ̀’ye a dágọ̀, orí imú ní fií gbé e kiri.


Yàtọ̀ sí gbólóhùn tí mo fà yọ nínú àwo rẹ́kọ́ọ̀dù kan tí ògbólógbòó onísákárà, olóògbé Yusuf Ọlátúnjí ṣe (n ò rántí ọdún náà mọ́), òwe ni gbogbo àwọn ìfáárà tí mo kọ sókè yìí. Ẹ ó sì mọ ìdí tí mo fi lò wọ́n bí ẹ bá ti ńka búlọ́ọ̀gì yìí síwájú sí i. 

Ikú lorúkọ tí à á pe títán ìmí fún gbogbo ẹ̀dá abẹ̀mí. Ènìyàn ńkú. Ẹrankó le kú. Ewéko le kú. Ọ̀pẹ á máa kú. Igi á máa a kú. Ṣùgbọ́n ilẹ̀ kìí kú. Ṣíṣá ni ilẹ̀ ńṣá. Èyí já sí pé ikú kọ́ lòpin ohun gbogbo. Òòrùn á máa wọ̀. Ṣùgbọ́n iná le kú, bó tilẹ̀ jẹ́ pé kìí ṣe abẹ̀mí bí àwọn yòókù tí a tò sílẹ̀ yìí! Èyí ṣe jẹ́? Kókó àkíyèsí ni wí pé ohun gbogbo tí ìmíi rẹ̀ bá bùṣe, tàbí tí okùnfà ìmíi rẹ̀ bá sé, (ìbá á jẹ́ ẹranko, ènìyàn, ewéko)  ni ikú pa.  Òfò ẹ̀mí ni ikú.

Ohunkóhun tó bá le kú tàbí lópin, kí ó sì di àfẹ́ẹ̀rí, máa ńmú ẹ̀dùn ọkàn wá. Èyí ni a máa ǹpè ní ọ̀fọ̀. Ọ̀fọ̀ kìí ṣe àpọ́nlé ikú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òwe kan sọ bẹ́ẹ̀. Ènìyàn tí ikú bá mu lọ kìí ṣọ̀fọ̀. Àwa tó kù lẹ́hìn ni ìdárò bá torí pé àwa là ńṣe àfẹ́rí ẹni wa tó ti lọ. Alààyè tí wíwà ẹní kú bá jẹ lógún ni ọ̀fọ́ ṣẹ̀. Ọ̀fọ̀ kìí ṣẹ ẹní kú. Àdánù ni ikú máa ńdá sílẹ̀ fún ẹni tí ńṣọ̀fọ̀. 

A lè fẹ àkíyèsí yìí lójú díẹ̀ sí i, kí á sọ pé ohunkóhun tí àìsíi rẹ̀ bá mú ni lọ́kàn ni a lè sọ pé ó kú. Ohun tí àìsíi rẹ̀ kò bá jẹ ni lọ́kàn, àgúnláa wọn. Ìdí rèé tí ètò ìyapa láàrin alààye àti ẹni àìsí fi jẹ́ káríayé; l’Áké, l’Ókò, títí tó fi dé Kọngbẹ. 

Gbogbo akitiyan ìyàkú àwa tó kù lẹ́yìn (fún àpẹrẹ, ayẹyẹ àti ìnáwó àṣèhìndè, ìdárò, títọ́jú orórì, ìgbàgbọ́ àjíǹde, ìlànà ogún jíjẹ, ìjórúkọ) dá lérí wíwá arọ́pò tàbí aṣojú fún ènìyàn tàbí ohun tí a pàdánùu rẹ̀. Ìrọ́pò ṣe pàtàkí gidigidi. Kò sí onímọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa ìhùwàsí ènìyàn tí èmi ka iṣẹ́ẹ rẹ̀ tí kò sọ pé ìrántí àti arò jẹ́ ohun tó tọ̀nà láti ṣe àárò ikú. Kódà, láyé àtijọ, olubi ni ìlú máa ńkà énìyàn tí ọ̀fọ̀ bá ṣẹ̀ tí kò dárò sí. Ìwadìí ìjìnlẹ̀ nípa ìhùwàsí ẹ̀dá sì ti fi yé ni pé a gbọ́dọ̀ bojú tó irú ẹni bẹ́ẹ̀. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọ́n le ṣe ìjàm̀bá fún ara wọn tàbí fún ẹlòmíràn.

Níkadìí, mo fẹ́ sọ pé ète sísọ àìrí di rírí, àìsí di wíwà, ẹ̀dùn di adùn, ènìyàn di ère, ni abájọ arò dídá. A máa ńkẹ́dùn ẹni (àti ohun) ìní tí a náání. Lẹ́hìn ikú, tàbí òpin, tàbí títán, ẹni (àti ohun) tí a náání, a máa ńmí ìmí ẹ̀dùn, a máa ńpohùnréré ẹkún, a máa ńsun ẹkún àsunùndákẹ́, a máa ńro àròkàn, a máa ńṣípà, a sì tún máa ńṣe ìdárò oríṣiríṣi.

Ó dìgbà kan na.

Comments

Popular posts from this blog

One Thought About Textual Beginnings: Ìbà

ÌJÚBÀ or ÌBÀ (noun); JÚBÀ (verb)   The initial gestures rendered to acknowledge authority figures, sacral or secular, to which a performance production owes its textual and institutional provenance constitute the ìjúbà (ìbà). The conventional words and motions thus presented demarcate the commencement of an iteration, pay homage to sources of influence and inspiration, praise past patronages, solicit audience support and understanding, wish failure for opposing will and interests, and outline the production’s goals. HISTORY Two paths stand out in the historical understanding of ìjúbà: one follows the older, text based line in translation manuals and dictionaries, and the other issues from scholarly studies of performance traditions. Although they are more recent and offer longer overviews that extend far back into mythical times, scholarly studies of ìjúbà lean heavily on old traditions recounted in explanations of contemporary enactments, mainly of egúngún and gẹ̀lẹ̀de...

Aṣọ Tòun Tènìyàn

Aṣọ Tàbí Ènìyàn? Lẹ́dà kan, mo gbọ́ pé, aṣọ ńlá kọ́ lènìyàn ńlá. Lẹ́dà kejì wọ́n tún fi yé mi pé aṣọ là ńkí, a à kí ‘nìyàn. (Ẹnu kòfẹ́sọ̀ àgbà kan ni mo tí kọ́kọ́ gbọ́ eléyìí ní nńkan bí ogún ọdún sẹ́hìn.) Èwo ni ká wá ṣe o? Èwo ni ká tẹ̀lé? Èwo ni ká gbàgbọ́. Gbólóhùn méjèèjì ha le jẹ́ òótọ́ bí? Àtakò kọ́ rèé! Ó dá mi lójú pé àfiwé ni gbólóhùn méjèèjì. A tilẹ̀ lè pé wọ́n lówe. Gbogbo wa la sì mọ̀ pé àfiwé kìí ṣe òfin. Àfiwé yàtọ̀ sí ìṣẹ̀dálẹ̀. Òwe kìí ṣe orò. Àfiwé le jẹ́ àbàláyé. Ṣùgbọ́n ọgbọ́n tàbí ìmọ̀ tí àfiwé bá gbéró máa ńyí padà lóòrè kóòrè. Òjó yàtọ̀ sí òjò. Mẹ́táfọ̀ yàtọ̀ sí òtítọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òtítọ́ lè farasin sínú mẹ́táfọ̀. Ẹ̀ràn yàtọ̀ sí irọ́.   Kò sí ẹ̀dá alààyè àti olóye kankan tí kò mọ̀ pé aṣọ kìí ṣe ènìyàn, tàbí wí pé ènìyàn yàtọ̀ sí aṣọ. Dídá lènìyàn ńdá aṣọ tàbí ẹ̀wù. A kìi dá ènìyàn bí ẹni ńdáṣọ. Ènìyàn lè wọ aṣọ tàbí ẹ̀wù. Èmi kò rò pé aṣọ lè wọ ènìyàn bí è...

Ebenezer Táíwò Adéẹ̀kọ́: 20 Years After & Notes Towards a Memoir

Ebenezer Táíwò Adéẹ̀kọ́ | 1918-2000 My father, E. Táíwò as he was called by many, left his home town at about the age of eight with something like a second grade education in his pocket. I am talking of Òdoláamẹ́sọ̀ of late 1920s to early 1930s. First, he moved to Ìjẹ̀bú Òde (Metropolitan Ìjẹ̀bú) to live with his uncle (the late S.J.O. Òtúbúṣẹ̀n, alias Bàbá Télọ̀) who realized quickly that schooling was not this boy’s thing and sent him further away to Lagos (!) to learn carpentry, one of the newer (historically speaking) building trades. After finishing his apprenticeship successfully and working for a while in Lagos, he followed the call of other relatives to move further away to Kano, in the “land of the Hausa” as we used to refer to Northern Nigeria generally even in my own childhood of the 1960s in south western Nigeria.  At the end of WWII, during which he worked as a rifle carpenter in Kano, he returned south to Ìbàdàn, where he lived the rest of his life....