Skip to main content

Orísun Ẹ̀tọ́

Photo: Ògbógi. by Adélékè Adéẹ̀kọ́













Lọ́sẹ̀ bíi mélòó kan sẹ́hìn, "Èrò Ni Gbẹ̀gìrì" ṣe ìlérí àgbéyẹ̀wò orísun ẹ̀tọ́. Bí iṣẹ́ kò bá pẹ́ ni, a kìí pẹ́ iṣẹ́.

1: Òfin jẹ́ orísun pàtàkì fún ẹ̀tọ́. Àwùjọ ẹ̀dá ni ó máa ńfòfin lélẹ̀ lórí ohun tí a lè ṣe, àti bí a ti lè ṣe wọ́n. Ohun tó bófin mu máa ńsábà jẹ́ ohun tó lẹ́tọ̀ọ́. Ohun tí ó lòdì sófin le má lẹ́tọ̀ọ́. Ènìyàn ni òfin máa ńdè. Òfin kìí mú igi, kìí mú ọ̀pẹ, kìi ́mú ẹranko. Òfin le mú olúwa àwọn nǹkan wọ̀nyí. (Bí ajá bá tilẹ̀ rò pé òun là ńbẹ̀rù, gbogbo wa la mọ̀ pé alájá là ńbọ̀wọ̀ fún.) Ẹ̀dá kankan kò lè ṣòfin fúnra rẹ̀ tàbí fún àwùjọ láì jẹ́ wípé ìlú fún un láṣẹ láti ṣe bẹ́ẹ̀. Èyí já sí pé òfin gbọdọ̀ ní àtìlẹ́hìn àṣẹ gbogboògbò. Ìlú, tàbí aláṣẹ, gbọdọ̀ lágbára láti lè mú òfin ṣẹ. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀tọ́ kò ní lójútùú. A lè pe òfin ní ìmúṣẹ ìfẹ́ ìlú tàbí àwùjọ.

2. Àṣà, tàbí gbogbo ìlànà ìbáṣepọ̀ tó bójúmu láwùjọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kìí ṣe òfin, le jẹ́ orísun ẹ̀tọ́. Fún àpẹrẹ, nígbà wo ló bójú mu láti dáná alẹ́? Nígbà wo làá pàlọ́? Irú oúnjẹ wo ni Mùsùlùmí lè fi túnu ààwẹ̀? Irú ẹ̀wù wo làá wọ̀ lọ síbi iṣẹ́? Ìbójú mu ní òṣùnwọ̀n àṣà. Ohun tó bá bójú mu, a máa bá ẹ̀tọ́ mu. Ènìyàn tí kò mọjú ti kò mọra le má rú òfin rárá; ṣùgbọ́n aláìmẹ̀tọ́ ní onítọ̀hún. Bí ó tilẹ̀ jẹ pé òbí tí kò bá tọ́mọ sọ́nà ńṣàìtọ́, ó ṣeéṣe kí irú ẹni bẹ́ẹ̀ má rú òfin kankan. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèwọ̀ jẹ mọ́ àṣà. A lè fi ìlànà ẹ̀sìn, ojúṣe, orò, ìṣẹ̀dálẹ̀, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, sábẹ́ ìsọ̀rì àṣà. 

3. Ẹ̀rí ọkàn ni aláyélùwà ẹ̀tọ́. Èyí ṣe jẹ́? Ẹ̀rí ọkàn ni alákòóso agbára, ìfẹ́, àti ìṣe. A máa ńrú òfin tí ẹ̀rí ọkàn bá sọ fún ni pé òfin ọ̀hún kò bá ẹ̀tọ́ mu. Fún àpẹrẹ, gbogbo òfin amúnisìn lòdí sí ẹ̀tọ́ torí ìpalára tí wọ́n máa ńṣe fún ìgbésí ayé ọmọ ènìyàn. Àìlẹ́tọ̀ọ́ rọ̀ mọ́ gbogbo àṣà tí kò bá bọ̀wọ̀ fún ọmọnìyàn, tí ẹ̀rí ọkàn fi yé ni pé ó ńfa ìnira àìmọwọ́-àìmẹsẹ̀, ìrẹ̀wẹ̀sì, ìrẹ́nijẹ, tàbí ìbànújẹ́. Ẹ̀rí ọkàn a máa darí wa láti kọ ẹ̀yìn sí òfin tàbí àṣà tó gba irúfẹ́ ìwà àti ìṣe bẹ́ẹ̀ láyè.

Lọ́sẹ̀ tó ńbọ̀, ìjíròrò wa yóò dá lérí ikú. Ó dìgbà kan ná. Láyọ̀ o.

Comments

Popular posts from this blog

One Thought About Textual Beginnings: Ìbà

ÌJÚBÀ or ÌBÀ (noun); JÚBÀ (verb)   The initial gestures rendered to acknowledge authority figures, sacral or secular, to which a performance production owes its textual and institutional provenance constitute the ìjúbà (ìbà). The conventional words and motions thus presented demarcate the commencement of an iteration, pay homage to sources of influence and inspiration, praise past patronages, solicit audience support and understanding, wish failure for opposing will and interests, and outline the production’s goals. HISTORY Two paths stand out in the historical understanding of ìjúbà: one follows the older, text based line in translation manuals and dictionaries, and the other issues from scholarly studies of performance traditions. Although they are more recent and offer longer overviews that extend far back into mythical times, scholarly studies of ìjúbà lean heavily on old traditions recounted in explanations of contemporary enactments, mainly of egúngún and gẹ̀lẹ̀de...

Aṣọ Tòun Tènìyàn

Aṣọ Tàbí Ènìyàn? Lẹ́dà kan, mo gbọ́ pé, aṣọ ńlá kọ́ lènìyàn ńlá. Lẹ́dà kejì wọ́n tún fi yé mi pé aṣọ là ńkí, a à kí ‘nìyàn. (Ẹnu kòfẹ́sọ̀ àgbà kan ni mo tí kọ́kọ́ gbọ́ eléyìí ní nńkan bí ogún ọdún sẹ́hìn.) Èwo ni ká wá ṣe o? Èwo ni ká tẹ̀lé? Èwo ni ká gbàgbọ́. Gbólóhùn méjèèjì ha le jẹ́ òótọ́ bí? Àtakò kọ́ rèé! Ó dá mi lójú pé àfiwé ni gbólóhùn méjèèjì. A tilẹ̀ lè pé wọ́n lówe. Gbogbo wa la sì mọ̀ pé àfiwé kìí ṣe òfin. Àfiwé yàtọ̀ sí ìṣẹ̀dálẹ̀. Òwe kìí ṣe orò. Àfiwé le jẹ́ àbàláyé. Ṣùgbọ́n ọgbọ́n tàbí ìmọ̀ tí àfiwé bá gbéró máa ńyí padà lóòrè kóòrè. Òjó yàtọ̀ sí òjò. Mẹ́táfọ̀ yàtọ̀ sí òtítọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òtítọ́ lè farasin sínú mẹ́táfọ̀. Ẹ̀ràn yàtọ̀ sí irọ́.   Kò sí ẹ̀dá alààyè àti olóye kankan tí kò mọ̀ pé aṣọ kìí ṣe ènìyàn, tàbí wí pé ènìyàn yàtọ̀ sí aṣọ. Dídá lènìyàn ńdá aṣọ tàbí ẹ̀wù. A kìi dá ènìyàn bí ẹni ńdáṣọ. Ènìyàn lè wọ aṣọ tàbí ẹ̀wù. Èmi kò rò pé aṣọ lè wọ ènìyàn bí è...

Biyi Bandele (1967-2022): In Memoriam

  Biyi Bandele (1967-2022): In Memoriam Biyi Bandele was a generous soul who never failed to give all he could to make others richer. His gifts in fiction writing and filmmaking are immortalized in the many works he authored and produced. The yet to be curated monumental record he made in the last two years with captivating photographs of innocence and experience around Lagos markets and waters will perhaps last longest. From those countless images on Biyi Bandele’s facebook page, I have selected the following painterly shots to begin to consecrate our memory of his enriching our lives. 1: Resting Boats, Ikoyi Island. (16 April 2021) ( https://www.facebook.com/profile/581568922/search/?q=ebute%20aro ) After seeing this image, I commented thus on April 16, 2021: “This is "Èbúté Aró" (Indigo Harbor). No doubt. And I beg to be allowed to be unanimous with myself regarding that. Heaven knows you have good eyes. Pardon my speaking in tongues! ”  2: Market People, Lagos Islan...